Traducción Yoruba - Abu Rahima Mikael
Traducción de los significados del Sagrado Corán
Traducida por Sheij Abu Rahima Michael Aikueyeni.
وَٱلضُّحَىٰ
Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.
وَٱلَّيۡلِ إِذَا سَجَىٰ
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.
مَا وَدَّعَكَ رَبُّكَ وَمَا قَلَىٰ
Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.
وَلَلۡأٓخِرَةُ خَيۡرٞ لَّكَ مِنَ ٱلۡأُولَىٰ
Dájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.
وَلَسَوۡفَ يُعۡطِيكَ رَبُّكَ فَتَرۡضَىٰٓ
Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.
أَلَمۡ يَجِدۡكَ يَتِيمٗا فَـَٔاوَىٰ
Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.
وَوَجَدَكَ ضَآلّٗا فَهَدَىٰ
Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]
وَوَجَدَكَ عَآئِلٗا فَأَغۡنَىٰ
Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.
فَأَمَّا ٱلۡيَتِيمَ فَلَا تَقۡهَرۡ
Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).
وَأَمَّا ٱلسَّآئِلَ فَلَا تَنۡهَرۡ
Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).
وَأَمَّا بِنِعۡمَةِ رَبِّكَ فَحَدِّثۡ
Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.
share_via