Yorba Dilinde Tercüme - Ebu Rahime Mikail
Kur'an-ı Kerim Anlamları Meali
Şeyh Ebu Rahime Mikail İykuviyni tarafından tercüme edilmiştir.
وَٱلتِّينِ وَٱلزَّيۡتُونِ
Allāhu fi èso tīn àti èso zaetūn búra.
وَطُورِ سِينِينَ
Ó tún fi àpáta Sīnīn búra.
وَهَٰذَا ٱلۡبَلَدِ ٱلۡأَمِينِ
Ó tún fi ìlú ìfàyàbalẹ̀ yìí búra.
لَقَدۡ خَلَقۡنَا ٱلۡإِنسَٰنَ فِيٓ أَحۡسَنِ تَقۡوِيمٖ
Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn pẹ̀lú ìrísí tó dára jùlọ.
ثُمَّ رَدَدۡنَٰهُ أَسۡفَلَ سَٰفِلِينَ
Lẹ́yìn náà, A máa dá a padà sí ìsàlẹ̀ pátápátá (nínú Iná).
إِلَّا ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَعَمِلُواْ ٱلصَّٰلِحَٰتِ فَلَهُمۡ أَجۡرٌ غَيۡرُ مَمۡنُونٖ
Àyàfi àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere. Nítorí náà, ẹ̀san tí kò níí pin (tí kò níí pẹ̀dín) ń bẹ fún wọn.
فَمَا يُكَذِّبُكَ بَعۡدُ بِٱلدِّينِ
Ta l’ó tún ń pè ọ́ ní òpùrọ́ nípa Ọjọ́ ẹ̀san lẹ́yìn (ọ̀rọ̀ yìí)?
أَلَيۡسَ ٱللَّهُ بِأَحۡكَمِ ٱلۡحَٰكِمِينَ
Ṣé Allāhu kọ́ ni Ẹni t’Ó mọ ẹ̀jọ́ dá jùlọ nínú àwọn adájọ́ ni?
share_via