Header Include

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

QR Code https://quran.islamcontent.com/ar/yoruba_mikail

وَٱلسَّمَآءِ ذَاتِ ٱلۡبُرُوجِ

(Allāhu) fi sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀ búra.

(Allāhu) fi sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀ búra.

وَٱلۡيَوۡمِ ٱلۡمَوۡعُودِ

Ó tún fi ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn (ìyẹn Ọjọ́ Àjíǹde) búra.

Ó tún fi ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn (ìyẹn Ọjọ́ Àjíǹde) búra.

وَشَاهِدٖ وَمَشۡهُودٖ

Ó tún fi olùjẹ́rìí àti ohun tó jẹ́rìí sí búra.

Ó tún fi olùjẹ́rìí àti ohun tó jẹ́rìí sí búra.

قُتِلَ أَصۡحَٰبُ ٱلۡأُخۡدُودِ

A ṣẹ́bi lé àwọn tó gbẹ́ kòtò (iná),

A ṣẹ́bi lé àwọn tó gbẹ́ kòtò (iná),

ٱلنَّارِ ذَاتِ ٱلۡوَقُودِ

(ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).

(ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).

إِذۡ هُمۡ عَلَيۡهَا قُعُودٞ

(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.

(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.

وَهُمۡ عَلَىٰ مَا يَفۡعَلُونَ بِٱلۡمُؤۡمِنِينَ شُهُودٞ

Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

وَمَا نَقَمُواْ مِنۡهُمۡ إِلَّآ أَن يُؤۡمِنُواْ بِٱللَّهِ ٱلۡعَزِيزِ ٱلۡحَمِيدِ

Wọn kò rí àlèébù kan (wọn kò sì kórira kiní kan) lára wọn bí kò ṣe pé, wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ẹlẹ́yìn,

Wọn kò rí àlèébù kan (wọn kò sì kórira kiní kan) lára wọn bí kò ṣe pé, wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ẹlẹ́yìn,

ٱلَّذِي لَهُۥ مُلۡكُ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلۡأَرۡضِۚ وَٱللَّهُ عَلَىٰ كُلِّ شَيۡءٖ شَهِيدٌ

Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.

Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.

إِنَّ ٱلَّذِينَ فَتَنُواْ ٱلۡمُؤۡمِنِينَ وَٱلۡمُؤۡمِنَٰتِ ثُمَّ لَمۡ يَتُوبُواْ فَلَهُمۡ عَذَابُ جَهَنَّمَ وَلَهُمۡ عَذَابُ ٱلۡحَرِيقِ

Dájúdájú àwọn tó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná tó ń jó sì wà fún wọn.

Dájúdájú àwọn tó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná tó ń jó sì wà fún wọn.

إِنَّ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَعَمِلُواْ ٱلصَّٰلِحَٰتِ لَهُمۡ جَنَّٰتٞ تَجۡرِي مِن تَحۡتِهَا ٱلۡأَنۡهَٰرُۚ ذَٰلِكَ ٱلۡفَوۡزُ ٱلۡكَبِيرُ

Dájúdájú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.

Dájúdájú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.

إِنَّ بَطۡشَ رَبِّكَ لَشَدِيدٌ

Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.

Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.

إِنَّهُۥ هُوَ يُبۡدِئُ وَيُعِيدُ

Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).

Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).

وَهُوَ ٱلۡغَفُورُ ٱلۡوَدُودُ

Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),

Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),

ذُو ٱلۡعَرۡشِ ٱلۡمَجِيدُ

Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ológo (Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ),

Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ológo (Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ),

فَعَّالٞ لِّمَا يُرِيدُ

Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.

Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.

هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ ٱلۡجُنُودِ

Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,

Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,

فِرۡعَوۡنَ وَثَمُودَ

(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?

(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?

بَلِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ فِي تَكۡذِيبٖ

Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo ní irọ́.

Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo ní irọ́.

وَٱللَّهُ مِن وَرَآئِهِم مُّحِيطُۢ

Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.

Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.

بَلۡ هُوَ قُرۡءَانٞ مَّجِيدٞ

Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,

Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,

فِي لَوۡحٖ مَّحۡفُوظِۭ

tí ó wà nínú wàláà tí wọ́n ń ṣọ́.

tí ó wà nínú wàláà tí wọ́n ń ṣọ́.
Footer Include