Header Include

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

QR Code https://quran.islamcontent.com/ar/yoruba_mikail

هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ ٱلۡغَٰشِيَةِ

Ṣebí ọ̀rọ̀ nípa ohun tó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

Ṣebí ọ̀rọ̀ nípa ohun tó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٍ خَٰشِعَةٌ

Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.

Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.

عَامِلَةٞ نَّاصِبَةٞ

Wọ́n ṣe iṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni nílé ayé).

Wọ́n ṣe iṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni nílé ayé).

تَصۡلَىٰ نَارًا حَامِيَةٗ

Wọ́n sì máa wọ inú Iná tó gbóná janjan (ní ọ̀run).

Wọ́n sì máa wọ inú Iná tó gbóná janjan (ní ọ̀run).

تُسۡقَىٰ مِنۡ عَيۡنٍ ءَانِيَةٖ

Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi ìṣẹ́lẹ̀rú gbígbóná mu.

Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi ìṣẹ́lẹ̀rú gbígbóná mu.

لَّيۡسَ لَهُمۡ طَعَامٌ إِلَّا مِن ضَرِيعٖ

Kò sí oúnjẹ kan fún wọn àyàfi igi ẹlẹ́gùn-ún gbígbẹ.

Kò sí oúnjẹ kan fún wọn àyàfi igi ẹlẹ́gùn-ún gbígbẹ.

لَّا يُسۡمِنُ وَلَا يُغۡنِي مِن جُوعٖ

Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.

Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.

وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاعِمَةٞ

Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn

Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn

لِّسَعۡيِهَا رَاضِيَةٞ

nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.

nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.

فِي جَنَّةٍ عَالِيَةٖ

(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.

(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.

لَّا تَسۡمَعُ فِيهَا لَٰغِيَةٗ

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.

فِيهَا عَيۡنٞ جَارِيَةٞ

Omi ìṣẹ́lẹ̀rú tó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.

Omi ìṣẹ́lẹ̀rú tó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.

فِيهَا سُرُرٞ مَّرۡفُوعَةٞ

Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,

Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,

وَأَكۡوَابٞ مَّوۡضُوعَةٞ

àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),

àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),

وَنَمَارِقُ مَصۡفُوفَةٞ

àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,

àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,

وَزَرَابِيُّ مَبۡثُوثَةٌ

àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.

àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.

أَفَلَا يَنظُرُونَ إِلَى ٱلۡإِبِلِ كَيۡفَ خُلِقَتۡ

Nítorí náà, ṣé wọn kò wòye sí ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;

Nítorí náà, ṣé wọn kò wòye sí ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;

وَإِلَى ٱلسَّمَآءِ كَيۡفَ رُفِعَتۡ

àti sánmọ̀, bí A ti ṣe gbé e sókè;

àti sánmọ̀, bí A ti ṣe gbé e sókè;

وَإِلَى ٱلۡجِبَالِ كَيۡفَ نُصِبَتۡ

àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);

àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);

وَإِلَى ٱلۡأَرۡضِ كَيۡفَ سُطِحَتۡ

àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ pẹrẹsẹ?

àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ pẹrẹsẹ?

فَذَكِّرۡ إِنَّمَآ أَنتَ مُذَكِّرٞ

Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.

Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.

لَّسۡتَ عَلَيۡهِم بِمُصَيۡطِرٍ

Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn

Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn

إِلَّا مَن تَوَلَّىٰ وَكَفَرَ

àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.

àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.

فَيُعَذِّبُهُ ٱللَّهُ ٱلۡعَذَابَ ٱلۡأَكۡبَرَ

Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà tó tóbi jùlọ.

Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà tó tóbi jùlọ.

إِنَّ إِلَيۡنَآ إِيَابَهُمۡ

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.

ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا حِسَابَهُم

Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.

Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.
Footer Include