Header Include

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

QR Code https://quran.islamcontent.com/ar/yoruba_mikail

وَٱلۡعَٰدِيَٰتِ ضَبۡحٗا

Allāhu fi àwọn ẹṣin tó ń sáré tó ń mí hẹlẹhẹlẹ ní ojú-ogun búra.

Allāhu fi àwọn ẹṣin tó ń sáré tó ń mí hẹlẹhẹlẹ ní ojú-ogun búra.

فَٱلۡمُورِيَٰتِ قَدۡحٗا

Ó tún fi àwọn ẹṣin tí pátákò ẹsẹ̀ wọn ń ṣáná (níbi eré sísá) búra.

Ó tún fi àwọn ẹṣin tí pátákò ẹsẹ̀ wọn ń ṣáná (níbi eré sísá) búra.

فَٱلۡمُغِيرَٰتِ صُبۡحٗا

Ó tún fi àwọn ẹṣin tó ń kọlu ọ̀tá ẹ̀sìn ní òwúrọ̀ kùtùkùtù búra.

Ó tún fi àwọn ẹṣin tó ń kọlu ọ̀tá ẹ̀sìn ní òwúrọ̀ kùtùkùtù búra.

فَأَثَرۡنَ بِهِۦ نَقۡعٗا

Wọ́n sì fi (pátákò ẹsẹ̀ wọn) tu eruku (ilẹ̀ ọ̀tá) sókè.

Wọ́n sì fi (pátákò ẹsẹ̀ wọn) tu eruku (ilẹ̀ ọ̀tá) sókè.

فَوَسَطۡنَ بِهِۦ جَمۡعًا

Wọ́n tún bẹ́ gìjà pẹ̀lú eruku ẹsẹ̀ wọn sáààrin àkójọ ọ̀tá.

Wọ́n tún bẹ́ gìjà pẹ̀lú eruku ẹsẹ̀ wọn sáààrin àkójọ ọ̀tá.

إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ لِرَبِّهِۦ لَكَنُودٞ

Dájúdájú ènìyàn ni aláìmoore sí Olúwa rẹ̀.

Dájúdájú ènìyàn ni aláìmoore sí Olúwa rẹ̀.

وَإِنَّهُۥ عَلَىٰ ذَٰلِكَ لَشَهِيدٞ

Dájúdájú Allāhu sì ń jẹ́ Ẹlẹ́rìí lórí ìyẹn.

Dájúdájú Allāhu sì ń jẹ́ Ẹlẹ́rìí lórí ìyẹn.

وَإِنَّهُۥ لِحُبِّ ٱلۡخَيۡرِ لَشَدِيدٌ

Àti pé dájúdájú ènìyàn le gan-an níbi ìfẹ́ oore ayé.

Àti pé dájúdájú ènìyàn le gan-an níbi ìfẹ́ oore ayé.

۞ أَفَلَا يَعۡلَمُ إِذَا بُعۡثِرَ مَا فِي ٱلۡقُبُورِ

Ṣé kò mọ̀ pé nígbà tí wọ́n bá tú ohun tó wà nínú sàréè jáde (fún àjíǹde),

Ṣé kò mọ̀ pé nígbà tí wọ́n bá tú ohun tó wà nínú sàréè jáde (fún àjíǹde),

وَحُصِّلَ مَا فِي ٱلصُّدُورِ

tí wọ́n sì tú ohun tó wà nínú igbá-àyà ẹ̀dá síta pátápátá,

tí wọ́n sì tú ohun tó wà nínú igbá-àyà ẹ̀dá síta pátápátá,

إِنَّ رَبَّهُم بِهِمۡ يَوۡمَئِذٖ لَّخَبِيرُۢ

dájúdájú Olúwa wọn ni Alámọ̀tán nípa wọn ní Ọjọ́ yẹn?

dájúdájú Olúwa wọn ni Alámọ̀tán nípa wọn ní Ọjọ́ yẹn?
Footer Include