约鲁巴语翻译 - 艾布·拉西麦·米卡依赖。

《古兰经》含义翻译

谢赫艾布·拉西麦·米卡依赖·艾奎尼翻译。

QR Code https://quran.islamcontent.com/zh/yoruba_mikail

وَٱلضُّحَىٰ

Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.

Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.

وَٱلَّيۡلِ إِذَا سَجَىٰ

Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.

Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.

مَا وَدَّعَكَ رَبُّكَ وَمَا قَلَىٰ

Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.

Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.

وَلَلۡأٓخِرَةُ خَيۡرٞ لَّكَ مِنَ ٱلۡأُولَىٰ

Dájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.

Dájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.

وَلَسَوۡفَ يُعۡطِيكَ رَبُّكَ فَتَرۡضَىٰٓ

Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.

Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.

أَلَمۡ يَجِدۡكَ يَتِيمٗا فَـَٔاوَىٰ

Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.

Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.

وَوَجَدَكَ ضَآلّٗا فَهَدَىٰ

Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]

[1] Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah aṣ-Ṣūrọ̄; 42:52.
Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]

وَوَجَدَكَ عَآئِلٗا فَأَغۡنَىٰ

Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.

Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.

فَأَمَّا ٱلۡيَتِيمَ فَلَا تَقۡهَرۡ

Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).

Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).

وَأَمَّا ٱلسَّآئِلَ فَلَا تَنۡهَرۡ

Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).

Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).

وَأَمَّا بِنِعۡمَةِ رَبِّكَ فَحَدِّثۡ

Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.

Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.