Header Include

الترجمة اليورباوية - أبو رحيمة ميكائيل

ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني.

QR Code https://quran.islamcontent.com/68/yoruba_mikail

لَآ أُقۡسِمُ بِهَٰذَا ٱلۡبَلَدِ

Èmi (Allāhu) ń fi ìlú yìí[1] búra.

[1] Allāhu lè fi ohunkóhun búra, àmọ́ fífi Allāhu nìkan ṣoṣo búra ni ẹ̀sìn gbà àwa láyè mọ láti fi búra. Bíbá Allāhu wá akẹgbẹ́ (ẹbọ ṣíṣe) sì ni fífi n̄ǹkan mìíràn búra lẹ́yìn Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā -.
Èmi (Allāhu) ń fi ìlú yìí[1] búra.

وَأَنتَ حِلُّۢ بِهَٰذَا ٱلۡبَلَدِ

Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).[1]

[1] Ẹ̀tọ́ tí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - fún Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ni kíkógun ja ìlú Mọkkah lásìkò ogun Ìṣí Mọkkah “Fat-hu Mọkkah”. Ṣíwájú àsìkò yìí àti lẹ́yìn rẹ̀, kò lẹ́tọ̀ọ́ fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti jagun nínú ìlú Mọkkah alápọ̀n-ọ́nlé.
Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).[1]

وَوَالِدٖ وَمَا وَلَدَ

Èmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.

Èmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.

لَقَدۡ خَلَقۡنَا ٱلۡإِنسَٰنَ فِي كَبَدٍ

Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.

Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.

أَيَحۡسَبُ أَن لَّن يَقۡدِرَ عَلَيۡهِ أَحَدٞ

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?

يَقُولُ أَهۡلَكۡتُ مَالٗا لُّبَدًا

Ó (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”

Ó (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”

أَيَحۡسَبُ أَن لَّمۡ يَرَهُۥٓ أَحَدٌ

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?

Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?

أَلَمۡ نَجۡعَل لَّهُۥ عَيۡنَيۡنِ

Ṣé A kò ṣe ojú méjì fún un?

Ṣé A kò ṣe ojú méjì fún un?

وَلِسَانٗا وَشَفَتَيۡنِ

Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?

Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?

وَهَدَيۡنَٰهُ ٱلنَّجۡدَيۡنِ

A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.

A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.

فَلَا ٱقۡتَحَمَ ٱلۡعَقَبَةَ

Kò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!

Kò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!

وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا ٱلۡعَقَبَةُ

Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?

Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?

فَكُّ رَقَبَةٍ

(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.

(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.

أَوۡ إِطۡعَٰمٞ فِي يَوۡمٖ ذِي مَسۡغَبَةٖ

Tàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.

Tàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.

يَتِيمٗا ذَا مَقۡرَبَةٍ

(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,

(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,

أَوۡ مِسۡكِينٗا ذَا مَتۡرَبَةٖ

tàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).

tàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).

ثُمَّ كَانَ مِنَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُواْ وَتَوَاصَوۡاْ بِٱلصَّبۡرِ وَتَوَاصَوۡاْ بِٱلۡمَرۡحَمَةِ

Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.

Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.

أُوْلَٰٓئِكَ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَيۡمَنَةِ

Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.

Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.

وَٱلَّذِينَ كَفَرُواْ بِـَٔايَٰتِنَا هُمۡ أَصۡحَٰبُ ٱلۡمَشۡـَٔمَةِ

Àwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.[1]

[1] Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:7.
Àwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.[1]

عَلَيۡهِمۡ نَارٞ مُّؤۡصَدَةُۢ

Wọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.

Wọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.
Footer Include