La traduction en yorouba - Aboû Raḥîmah Mickaël
Traduction des sens du Noble Coran
Traduit par Cheikh Aboû Raḥîmah Mickaël Aykwînî.
أَلۡهَىٰكُمُ ٱلتَّكَاثُرُ
Wíwá oore ayé ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ fún ìyanràn ṣíṣe ti kó àìrójú fẹ́sìn ba yín
حَتَّىٰ زُرۡتُمُ ٱلۡمَقَابِرَ
títí ẹ fi wọ inú sàréè.
كَلَّا سَوۡفَ تَعۡلَمُونَ
Rárá (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀, àmọ́) láìpẹ́ ẹ máa mọ̀.
ثُمَّ كَلَّا سَوۡفَ تَعۡلَمُونَ
Lẹ́yìn náà, ní ti òdodo, láìpẹ́ ẹ máa mọ̀.
كَلَّا لَوۡ تَعۡلَمُونَ عِلۡمَ ٱلۡيَقِينِ
Ní ti òdodo, tí ó bá jẹ́ pé ẹ ni ìmọ̀ àmọ̀dájú ni (ẹ̀yin ìbá tí ṣe bẹ́ẹ̀).
لَتَرَوُنَّ ٱلۡجَحِيمَ
Dájúdájú ẹ máa rí iná Jẹhīm.
ثُمَّ لَتَرَوُنَّهَا عَيۡنَ ٱلۡيَقِينِ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ máa fi ojú rí i ní àrídájú.
ثُمَّ لَتُسۡـَٔلُنَّ يَوۡمَئِذٍ عَنِ ٱلنَّعِيمِ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ní ọjọ́ yẹn wọ́n máa bi yín léèrè nípa ìgbádùn (ayé yìí).
share_via