یوربایي ژباړه
یوربا ژبې ته د قرآن کریم د معناګانو ژباړه، ژباړوونکی: الشیخ ابو رحیمة میکائیل ایکوییني. چاپ کال ۱۴۳۲ هـ.
قُلۡ أَعُوذُ بِرَبِّ ٱلۡفَلَقِ
Sọ pé: “Mo sá di Olúwa òwúrọ̀ kùtùkùtù
Sọ pé: “Mo sá di Olúwa òwúrọ̀ kùtùkùtù
مِن شَرِّ مَا خَلَقَ
níbi aburú ohun tí Ó dá,¹
1. Allāhu ni Ẹlẹ́dàá gbogbo n̄ǹkan, ohun rere àti ohun burúkú. Ọ̀kan pàtàkì nínú ohun burúkú nínú àwọn ẹ̀dá tí Allāhu dá ni aṣ-Ṣaetọ̄n àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ bí àjẹ́, oṣó, emèrè, àwọn n̄ǹkan olóró àti àwọn iwọ. Nítorí náà, Èṣù kọ́ ló dá owó àti dúkìá. Ẹni tí ó bá wá tọrọ owó ní ọ̀dọ̀ Èṣù, ó ti di ẹlẹ́bọ, ẹni Èṣù.
níbi aburú ohun tí Ó dá,¹
وَمِن شَرِّ غَاسِقٍ إِذَا وَقَبَ
àti níbi aburú òru nígbà tí ó bá ṣóòkùn,
àti níbi aburú òru nígbà tí ó bá ṣóòkùn,
وَمِن شَرِّ ٱلنَّفَّٰثَٰتِ فِي ٱلۡعُقَدِ
àti níbi aburú àwọn (òpìdán) tó ń fẹnu fátẹ́gùn túẹ́túẹ́ sínú àwọn ońdè,
àti níbi aburú àwọn (òpìdán) tó ń fẹnu fátẹ́gùn túẹ́túẹ́ sínú àwọn ońdè,
وَمِن شَرِّ حَاسِدٍ إِذَا حَسَدَ
àti níbi aburú onílara nígbà tí ó bá ṣe ìlara.”
àti níbi aburú onílara nígbà tí ó bá ṣe ìlara.”
مشاركة عبر