یوربایي ژباړه
یوربا ژبې ته د قرآن کریم د معناګانو ژباړه، ژباړوونکی: الشیخ ابو رحیمة میکائیل ایکوییني. چاپ کال ۱۴۳۲ هـ.
وَٱلشَّمۡسِ وَضُحَىٰهَا
Allāhu fi òòrùn àti ìyálẹ̀ta rẹ̀ búra.
وَٱلۡقَمَرِ إِذَا تَلَىٰهَا
Ó tún fi òṣùpá nígbà tí ó bá (yọ) tẹ̀lé (òòrùn) búra.
وَٱلنَّهَارِ إِذَا جَلَّىٰهَا
Ó tún fi ọ̀sán nígbà tí ó bá mú ìmọ́lẹ̀ bá òkùnkùn òru búra.
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَغۡشَىٰهَا
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá bo ọ̀sán mọ́lẹ̀ búra.
وَٱلسَّمَآءِ وَمَا بَنَىٰهَا
Ó tún fi sánmọ̀ àti Ẹni tí Ó mọ ọ́n¹ búra?
وَٱلۡأَرۡضِ وَمَا طَحَىٰهَا
Ó tún fi ilẹ̀ àti Ẹni tí Ó tẹ́ ẹ kalẹ̀ pẹrẹsẹ búra.
وَنَفۡسٖ وَمَا سَوَّىٰهَا
Ó tún fi ẹ̀mí (ènìyàn) àti Ẹni tí Ó ṣe (oríkèé rẹ̀) dọ́gba búra.
فَأَلۡهَمَهَا فُجُورَهَا وَتَقۡوَىٰهَا
Ó sì fi ẹ̀ṣẹ̀ (tí ẹ̀mí lè dá) àti ìbẹ̀rù rẹ̀ mọ̀ ọ́n.
قَدۡ أَفۡلَحَ مَن زَكَّىٰهَا
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe àfọ̀mọ́ (ẹ̀mí ara) rẹ̀ (níbi ẹ̀ṣẹ̀), ó mà ti jèrè.¹
وَقَدۡ خَابَ مَن دَسَّىٰهَا
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi (ìwà ẹ̀ṣẹ̀) ba ẹ̀mí (ara) rẹ̀ jẹ́, ó mà ti pàdánù.
كَذَّبَتۡ ثَمُودُ بِطَغۡوَىٰهَآ
Ìjọ Thamūd pe òdodo ní irọ́ nípa ìtayọ ẹnu-ààlà wọn.
إِذِ ٱنۢبَعَثَ أَشۡقَىٰهَا
(Rántí) nígbà tí ẹni tí orí rẹ̀ burú jùlọ nínú wọn sáré dìde (láti gún ràkúnmí pa).
فَقَالَ لَهُمۡ رَسُولُ ٱللَّهِ نَاقَةَ ٱللَّهِ وَسُقۡيَٰهَا
Nígbà náà, Òjíṣẹ́ Allāhu sọ fún wọn pé: “(Ẹ fi) abo ràkúnmí Allāhu àti omi rẹ̀ (sílẹ̀).”
فَكَذَّبُوهُ فَعَقَرُوهَا فَدَمۡدَمَ عَلَيۡهِمۡ رَبُّهُم بِذَنۢبِهِمۡ فَسَوَّىٰهَا
Wọ́n pè é ní òpùrọ́. Wọ́n sì gún (ràkúnmí) pa. Nítorí náà, Olúwa wọn pa wọ́n rẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ó sì fi ìparun náà kárí wọn.
وَلَا يَخَافُ عُقۡبَٰهَا
(Ẹni tó gún ràkúnmí pa) kò sì páyà ìkángun ọ̀rọ̀ wọn.
مشاركة عبر