Header Include

ترجمه ى یوروبایی

ترجمه ى معانی قرآن کریم به زبان یوروبایی. مترجم: شیخ ابو رحیمه میکائیل ایکوینی. سال چاپ: 1432هجرى قمرى.

QR Code https://quran.islamcontent.com/fa/yoruba_mikail

لَآ أُقۡسِمُ بِيَوۡمِ ٱلۡقِيَٰمَةِ

Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.

Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.

وَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلنَّفۡسِ ٱللَّوَّامَةِ

Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.

Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.

أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَلَّن نَّجۡمَعَ عِظَامَهُۥ

Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?

Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?

بَلَىٰ قَٰدِرِينَ عَلَىٰٓ أَن نُّسَوِّيَ بَنَانَهُۥ

Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.

1.Àwọn ọmọníka ọwọ́ àti ọmọníka ẹsẹ̀, ọ̀tún rẹ̀ àti òsì rẹ̀. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41.
Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.

بَلۡ يُرِيدُ ٱلۡإِنسَٰنُ لِيَفۡجُرَ أَمَامَهُۥ

Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀

Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀

يَسۡـَٔلُ أَيَّانَ يَوۡمُ ٱلۡقِيَٰمَةِ

ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”

ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”

فَإِذَا بَرِقَ ٱلۡبَصَرُ

Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,

Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,

وَخَسَفَ ٱلۡقَمَرُ

àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,

àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,

وَجُمِعَ ٱلشَّمۡسُ وَٱلۡقَمَرُ

àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,

àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,

يَقُولُ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذٍ أَيۡنَ ٱلۡمَفَرُّ

ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”

ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”

كَلَّا لَا وَزَرَ

Rárá, kò sí ibùsásí.

Rárá, kò sí ibùsásí.

إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمُسۡتَقَرُّ

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.

يُنَبَّؤُاْ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذِۭ بِمَا قَدَّمَ وَأَخَّرَ

Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).

Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).

بَلِ ٱلۡإِنسَٰنُ عَلَىٰ نَفۡسِهِۦ بَصِيرَةٞ

Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,

Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,

وَلَوۡ أَلۡقَىٰ مَعَاذِيرَهُۥ

ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.

ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.

لَا تُحَرِّكۡ بِهِۦ لِسَانَكَ لِتَعۡجَلَ بِهِۦٓ

Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.

Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.

إِنَّ عَلَيۡنَا جَمۡعَهُۥ وَقُرۡءَانَهُۥ

Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.

Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.

فَإِذَا قَرَأۡنَٰهُ فَٱتَّبِعۡ قُرۡءَانَهُۥ

Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.

Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.

ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا بَيَانَهُۥ

Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.

Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.

كَلَّا بَلۡ تُحِبُّونَ ٱلۡعَاجِلَةَ

Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.

Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.

وَتَذَرُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ

Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.

Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.

وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاضِرَةٌ

Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).

Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).

إِلَىٰ رَبِّهَا نَاظِرَةٞ

Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.

Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.

وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذِۭ بَاسِرَةٞ

Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.

Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.

تَظُنُّ أَن يُفۡعَلَ بِهَا فَاقِرَةٞ

(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.

(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.

كَلَّآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلتَّرَاقِيَ

Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.

Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.

وَقِيلَ مَنۡۜ رَاقٖ

A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?

A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?

وَظَنَّ أَنَّهُ ٱلۡفِرَاقُ

Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.

Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.

وَٱلۡتَفَّتِ ٱلسَّاقُ بِٱلسَّاقِ

Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.

Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.

إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمَسَاقُ

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.

فَلَا صَدَّقَ وَلَا صَلَّىٰ

Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.

Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.

وَلَٰكِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ

Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.

Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.

ثُمَّ ذَهَبَ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِۦ يَتَمَطَّىٰٓ

Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.

Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.

أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰ

(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.

(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.

ثُمَّ أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰٓ

Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.

Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.

أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَن يُتۡرَكَ سُدًى

Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?

Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?

أَلَمۡ يَكُ نُطۡفَةٗ مِّن مَّنِيّٖ يُمۡنَىٰ

Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?

Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?

ثُمَّ كَانَ عَلَقَةٗ فَخَلَقَ فَسَوَّىٰ

Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.

Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.

فَجَعَلَ مِنۡهُ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰٓ

(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.

(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.

أَلَيۡسَ ذَٰلِكَ بِقَٰدِرٍ عَلَىٰٓ أَن يُحۡـِۧيَ ٱلۡمَوۡتَىٰ

Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?

Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
Footer Include