Header Include

ترجمه ى یوروبایی

ترجمه ى معانی قرآن کریم به زبان یوروبایی. مترجم: شیخ ابو رحیمه میکائیل ایکوینی. سال چاپ: 1432هجرى قمرى.

QR Code https://quran.islamcontent.com/fa/yoruba_mikail

عَبَسَ وَتَوَلَّىٰٓ

Ó fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà¹

1. Ìyẹn ni pé, Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà.
Ó fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà¹

أَن جَآءَهُ ٱلۡأَعۡمَىٰ

nítorí pé afọ́jú wá bá a.

nítorí pé afọ́jú wá bá a.

وَمَا يُدۡرِيكَ لَعَلَّهُۥ يَزَّكَّىٰٓ

Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)

Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)

أَوۡ يَذَّكَّرُ فَتَنفَعَهُ ٱلذِّكۡرَىٰٓ

tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?

tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?

أَمَّا مَنِ ٱسۡتَغۡنَىٰ

Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,

Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,

فَأَنتَ لَهُۥ تَصَدَّىٰ

òun ni ìwọ tẹ́tí sí.

òun ni ìwọ tẹ́tí sí.

وَمَا عَلَيۡكَ أَلَّا يَزَّكَّىٰ

Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).

Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).

وَأَمَّا مَن جَآءَكَ يَسۡعَىٰ

Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, tó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),

Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, tó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),

وَهُوَ يَخۡشَىٰ

tí ó sì ń páyà (Allāhu),

tí ó sì ń páyà (Allāhu),

فَأَنتَ عَنۡهُ تَلَهَّىٰ

ìwọ kò sì kọbi ara sí i.

ìwọ kò sì kọbi ara sí i.

كَلَّآ إِنَّهَا تَذۡكِرَةٞ

Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.

Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.

فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ

Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.

Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.

فِي صُحُفٖ مُّكَرَّمَةٖ

(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,

(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,

مَّرۡفُوعَةٖ مُّطَهَّرَةِۭ

A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́

A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́

بِأَيۡدِي سَفَرَةٖ

ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),

ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),

كِرَامِۭ بَرَرَةٖ

àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.

àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.

قُتِلَ ٱلۡإِنسَٰنُ مَآ أَكۡفَرَهُۥ

Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!

Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!

مِنۡ أَيِّ شَيۡءٍ خَلَقَهُۥ

Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?

Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?

مِن نُّطۡفَةٍ خَلَقَهُۥ فَقَدَّرَهُۥ

Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.

Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.

ثُمَّ ٱلسَّبِيلَ يَسَّرَهُۥ

Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.

Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.

ثُمَّ أَمَاتَهُۥ فَأَقۡبَرَهُۥ

Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.

Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.

ثُمَّ إِذَا شَآءَ أَنشَرَهُۥ

Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.

Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.

كَلَّا لَمَّا يَقۡضِ مَآ أَمَرَهُۥ

Rárá o! Ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.

Rárá o! Ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.

فَلۡيَنظُرِ ٱلۡإِنسَٰنُ إِلَىٰ طَعَامِهِۦٓ

Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.

Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.

أَنَّا صَبَبۡنَا ٱلۡمَآءَ صَبّٗا

Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.

Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.

ثُمَّ شَقَقۡنَا ٱلۡأَرۡضَ شَقّٗا

Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.

Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.

فَأَنۢبَتۡنَا فِيهَا حَبّٗا

A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;

A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;

وَعِنَبٗا وَقَضۡبٗا

àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,

àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,

وَزَيۡتُونٗا وَنَخۡلٗا

àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,

àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,

وَحَدَآئِقَ غُلۡبٗا

àti àwọn ọgbà tó kún fún igi,

àti àwọn ọgbà tó kún fún igi,

وَفَٰكِهَةٗ وَأَبّٗا

àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).

àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).

مَّتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ

(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

فَإِذَا جَآءَتِ ٱلصَّآخَّةُ

Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,

Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,

يَوۡمَ يَفِرُّ ٱلۡمَرۡءُ مِنۡ أَخِيهِ

ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,

ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,

وَأُمِّهِۦ وَأَبِيهِ

àti ìyá rẹ̀ àti bàbá rẹ̀,

àti ìyá rẹ̀ àti bàbá rẹ̀,

وَصَٰحِبَتِهِۦ وَبَنِيهِ

àti ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀.

àti ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀.

لِكُلِّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ يَوۡمَئِذٖ شَأۡنٞ يُغۡنِيهِ

Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn tó máa tó o ó rán.

Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn tó máa tó o ó rán.

وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ مُّسۡفِرَةٞ

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.

ضَاحِكَةٞ مُّسۡتَبۡشِرَةٞ

Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.

Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.

وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذٍ عَلَيۡهَا غَبَرَةٞ

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.

Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.

تَرۡهَقُهَا قَتَرَةٌ

Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.

Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.

أُوْلَٰٓئِكَ هُمُ ٱلۡكَفَرَةُ ٱلۡفَجَرَةُ

Àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.

Àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
Footer Include