Header Include

ترجمه ى یوروبایی

ترجمه ى معانی قرآن کریم به زبان یوروبایی. مترجم: شیخ ابو رحیمه میکائیل ایکوینی. سال چاپ: 1432هجرى قمرى.

QR Code https://quran.islamcontent.com/fa/yoruba_mikail

ٱقۡرَأۡ بِٱسۡمِ رَبِّكَ ٱلَّذِي خَلَقَ

Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.

Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.

خَلَقَ ٱلۡإِنسَٰنَ مِنۡ عَلَقٍ

Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.

Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.

ٱقۡرَأۡ وَرَبُّكَ ٱلۡأَكۡرَمُ

Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.

Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.

ٱلَّذِي عَلَّمَ بِٱلۡقَلَمِ

Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.

Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.

عَلَّمَ ٱلۡإِنسَٰنَ مَا لَمۡ يَعۡلَمۡ

Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.

Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.

كَلَّآ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ لَيَطۡغَىٰٓ

Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-ààlà

Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-ààlà

أَن رَّءَاهُ ٱسۡتَغۡنَىٰٓ

nítorí pé ó rí ara rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.

nítorí pé ó rí ara rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.

إِنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ ٱلرُّجۡعَىٰٓ

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.

أَرَءَيۡتَ ٱلَّذِي يَنۡهَىٰ

Sọ fún mi nípa ẹni tó ń kọ̀

Sọ fún mi nípa ẹni tó ń kọ̀

عَبۡدًا إِذَا صَلَّىٰٓ

fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!

fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!

أَرَءَيۡتَ إِن كَانَ عَلَى ٱلۡهُدَىٰٓ

Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)

Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)

أَوۡ أَمَرَ بِٱلتَّقۡوَىٰٓ

tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!

tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!

أَرَءَيۡتَ إِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰٓ

Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?

Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo ní irọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?

أَلَمۡ يَعۡلَم بِأَنَّ ٱللَّهَ يَرَىٰ

Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)

Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)

كَلَّا لَئِن لَّمۡ يَنتَهِ لَنَسۡفَعَۢا بِٱلنَّاصِيَةِ

Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ọ̀tá Allāhu ṣe rò ó sí.¹) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí² rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);

1. Ẹni yẹn ni Abu Jahl. 2. àásó orí; irun iwájú orí.
Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ọ̀tá Allāhu ṣe rò ó sí.¹) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí² rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);

نَاصِيَةٖ كَٰذِبَةٍ خَاطِئَةٖ

àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.

àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.

فَلۡيَدۡعُ نَادِيَهُۥ

Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.

Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.

سَنَدۡعُ ٱلزَّبَانِيَةَ

Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.

Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.

كَلَّا لَا تُطِعۡهُ وَٱسۡجُدۡۤ وَٱقۡتَرِب۩

Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ó ṣe ń sọ nípa Wa). Má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o sì súnmọ́ (Allāhu).

Rárá (ọ̀rọ̀ kò rí bí ó ṣe ń sọ nípa Wa). Má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o sì súnmọ́ (Allāhu).
Footer Include