ヨルバ語対訳
クルアーン・ヨルバ語対訳 - Abu Rahima Mikhail Aikweiny ヒジュラ暦1432年印刷
وَٱلۡمُرۡسَلَٰتِ عُرۡفٗا
Allāhu fi àwọn atẹ́gùn tó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé búra.
فَٱلۡعَٰصِفَٰتِ عَصۡفٗا
Ó fi àwọn ìjì atẹ́gùn tó ń jà búra.
وَٱلنَّٰشِرَٰتِ نَشۡرٗا
Ó fi àwọn atẹ́gùn tó ń tú èṣújò ká búra.
فَٱلۡفَٰرِقَٰتِ فَرۡقٗا
Ó fi àwọn tó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́ búra.
فَٱلۡمُلۡقِيَٰتِ ذِكۡرًا
Ó fi àwọn mọlāika tó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́) búra.
عُذۡرًا أَوۡ نُذۡرًا
(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.
إِنَّمَا تُوعَدُونَ لَوَٰقِعٞ
Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fún yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.
فَإِذَا ٱلنُّجُومُ طُمِسَتۡ
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,
وَإِذَا ٱلسَّمَآءُ فُرِجَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,
وَإِذَا ٱلۡجِبَالُ نُسِفَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,
وَإِذَا ٱلرُّسُلُ أُقِّتَتۡ
àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ (pẹ̀lú ìjọ wọn),
لِأَيِّ يَوۡمٍ أُجِّلَتۡ
ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?
لِيَوۡمِ ٱلۡفَصۡلِ
Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلۡفَصۡلِ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
أَلَمۡ نُهۡلِكِ ٱلۡأَوَّلِينَ
Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?
ثُمَّ نُتۡبِعُهُمُ ٱلۡأٓخِرِينَ
Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).
كَذَٰلِكَ نَفۡعَلُ بِٱلۡمُجۡرِمِينَ
Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
أَلَمۡ نَخۡلُقكُّم مِّن مَّآءٖ مَّهِينٖ
Ṣé A kò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?
فَجَعَلۡنَٰهُ فِي قَرَارٖ مَّكِينٍ
Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)
إِلَىٰ قَدَرٖ مَّعۡلُومٖ
títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).
فَقَدَرۡنَا فَنِعۡمَ ٱلۡقَٰدِرُونَ
A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀. Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá tó dára.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ كِفَاتًا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun tó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;
أَحۡيَآءٗ وَأَمۡوَٰتٗا
(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?
وَجَعَلۡنَا فِيهَا رَوَٰسِيَ شَٰمِخَٰتٖ وَأَسۡقَيۡنَٰكُم مَّآءٗ فُرَاتٗا
A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fún yín ní omi dídùn mu.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
ٱنطَلِقُوٓاْ إِلَىٰ مَا كُنتُم بِهِۦ تُكَذِّبُونَ
Ẹ máa lọ sí ibi tí ẹ̀ ń pè ní irọ́.
ٱنطَلِقُوٓاْ إِلَىٰ ظِلّٖ ذِي ثَلَٰثِ شُعَبٖ
Ẹ máa lọ sí ibi èéfín ẹlẹ́ka mẹ́ta.
لَّا ظَلِيلٖ وَلَا يُغۡنِي مِنَ ٱللَّهَبِ
Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.
إِنَّهَا تَرۡمِي بِشَرَرٖ كَٱلۡقَصۡرِ
Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè tó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.
كَأَنَّهُۥ جِمَٰلَتٞ صُفۡرٞ
(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́
هَٰذَا يَوۡمُ لَا يَنطِقُونَ
Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.
وَلَا يُؤۡذَنُ لَهُمۡ فَيَعۡتَذِرُونَ
A kò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
هَٰذَا يَوۡمُ ٱلۡفَصۡلِۖ جَمَعۡنَٰكُمۡ وَٱلۡأَوَّلِينَ
Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.
فَإِن كَانَ لَكُمۡ كَيۡدٞ فَكِيدُونِ
Tí ẹ bá ní ète kan lọ́wọ́, ẹ déte sí Mi wò.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
إِنَّ ٱلۡمُتَّقِينَ فِي ظِلَٰلٖ وَعُيُونٖ
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,
وَفَوَٰكِهَ مِمَّا يَشۡتَهُونَ
àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.
كُلُواْ وَٱشۡرَبُواْ هَنِيٓـَٔۢا بِمَا كُنتُمۡ تَعۡمَلُونَ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجۡزِي ٱلۡمُحۡسِنِينَ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
كُلُواْ وَتَمَتَّعُواْ قَلِيلًا إِنَّكُم مُّجۡرِمُونَ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
وَإِذَا قِيلَ لَهُمُ ٱرۡكَعُواْ لَا يَرۡكَعُونَ
Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.
وَيۡلٞ يَوۡمَئِذٖ لِّلۡمُكَذِّبِينَ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
فَبِأَيِّ حَدِيثِۭ بَعۡدَهُۥ يُؤۡمِنُونَ
Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?¹
مشاركة عبر