ヨルバ語対訳
クルアーン・ヨルバ語対訳 - Abu Rahima Mikhail Aikweiny ヒジュラ暦1432年印刷
إِذَا ٱلسَّمَآءُ ٱنفَطَرَتۡ
Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,¹
وَإِذَا ٱلۡكَوَاكِبُ ٱنتَثَرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
وَإِذَا ٱلۡبِحَارُ فُجِّرَتۡ
àti nígbà tí àwọn ibúdò bá ṣàn jára wọn,
وَإِذَا ٱلۡقُبُورُ بُعۡثِرَتۡ
àti (nígbà tí A bá ta ilẹ̀ sókè), tí A sì mú àwọn òkú jáde (láàyè) láti inú àwọn sàréè,
عَلِمَتۡ نَفۡسٞ مَّا قَدَّمَتۡ وَأَخَّرَتۡ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan yóò mọ ohun tí ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tí ó fi sẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡإِنسَٰنُ مَا غَرَّكَ بِرَبِّكَ ٱلۡكَرِيمِ
Ìwọ ènìyàn, kí ni ó tàn ọ́ jẹ nípa Olúwa rẹ, Alápọ̀n-ọ́nlé,
ٱلَّذِي خَلَقَكَ فَسَوَّىٰكَ فَعَدَلَكَ
Ẹni t’Ó ṣẹ̀dá rẹ? Ó ṣẹ̀dá rẹ̀ ní pípé. Ó sì mú ọ dọ́gba jalẹ̀ léèyàn.
فِيٓ أَيِّ صُورَةٖ مَّا شَآءَ رَكَّبَكَ
Ó to ẹ̀yà ara rẹ papọ̀ sínú èyíkéyìí àwòrán tí Ó fẹ́.
كَلَّا بَلۡ تُكَذِّبُونَ بِٱلدِّينِ
Rárá! Bí kò ṣe pé ẹ̀ ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́.
وَإِنَّ عَلَيۡكُمۡ لَحَٰفِظِينَ
Dájúdájú àwọn ẹ̀ṣọ́ sì wà ní ọ̀dọ̀ yín.
كِرَامٗا كَٰتِبِينَ
(Wọ́n jẹ́) alápọ̀n-ọ́nlé, òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá.
يَعۡلَمُونَ مَا تَفۡعَلُونَ
Wọ́n mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
إِنَّ ٱلۡأَبۡرَارَ لَفِي نَعِيمٖ
Dájúdájú àwọn ẹni rere yóò kúkú wà nínú ìgbádùn.
وَإِنَّ ٱلۡفُجَّارَ لَفِي جَحِيمٖ
Dájúdájú àwọn ẹni ibi yó sì kúkú wà nínú iná Jẹhīm.
يَصۡلَوۡنَهَا يَوۡمَ ٱلدِّينِ
Wọn yóò wọ inú rẹ̀ ní Ọjọ́ ẹ̀san.
وَمَا هُمۡ عَنۡهَا بِغَآئِبِينَ
Wọn kò sì níí kúrò nínú rẹ̀.
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلدِّينِ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
ثُمَّ مَآ أَدۡرَىٰكَ مَا يَوۡمُ ٱلدِّينِ
Lẹ́yìn náà, kí ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
يَوۡمَ لَا تَمۡلِكُ نَفۡسٞ لِّنَفۡسٖ شَيۡـٔٗاۖ وَٱلۡأَمۡرُ يَوۡمَئِذٖ لِّلَّهِ
(Ọjọ́ ẹ̀san ni) ọjọ́ tí ẹ̀mí kan kò níí kápá kiní kan fún ẹ̀mí kan. Gbogbo àṣẹ ọjọ́ yẹn sì ń jẹ́ ti Allāhu.
مشاركة عبر